a Isa 15–16; Jr 48; El 25.8-11; Am 2.1-3; Sf 2.8-11.

Isaiah 25:10-12

10 aỌwọ́ Olúwa yóò sinmi lé orí òkè yìí
ṣùgbọ́n a ó tẹ Moabu mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀;
gẹ́gẹ́ bí a ti gún koríko mọ́lẹ̀ di ajílẹ̀.
11Wọn yóò na ọwọ́ wọn jáde nínú rẹ̀,
gẹ́gẹ́ bí òmùwẹ̀ tí ń na ọwọ́ rẹ̀
jáde láti lúwẹ̀ẹ́.
Ọlọ́run yóò mú ìgbéraga wọn wálẹ̀
bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìṣeféfé wà ní ọwọ́ wọn.
12Òun yóò sì bi gbogbo ògiri gíga alágbára yín lulẹ̀
wọn yóò sì wà nílẹ̀
Òun yóò sì mú wọn wá si ilẹ̀,
àní sí erùpẹ̀ lásán.
Copyright information for YorBMYO